• EWÍ — OMINIRA




    Lati Owo - Adedire Dare  

    Mebí wónni títa ríro laa kolà,bóbá jiná tán a doge

    Ojú kìípósin kómá là ni àwon àgbà únwí


    Emi lówá dé  tómìnira sewá doun ègàn nílèyí

    Òmìnira oun Omi ìnira kòwá yátò síra won ní naija únbí

    Terú tomo niwón ún kígbe ólekoko 

    Omo eléran wá n jegun,aláso n wo àkísà

    Àbámò wá gbenu terú tomo kan 


    Omase ooo, ayeye oríleèdè lé lódún làa ñ se   nílè yí lódodún, be eku òké bí eku,Omo èyàn oti foún bí èyàn

    Aatíi gbó pé Omo tólé lógóta odún kò kúrò nípò rírá bi Omo tuntun

    Aatíi gbó pé Omo olówó n toro oúnje je ni


    Èyin olórí nílèyí ,èyin ni mo bá léjó ,ebá wa tún lèyí se èbè labè ,ejè ajáwó nínú àpòn tí ò yò ká ya gbómi ilá kaná,eeyé paró yio da fúnwa

    Ojó wo gan nilèyí fé tèsíwájú ? eje n gbó

    Towon ó dòpò ní salaria tiwa

    Teerin ágbenu mùtúmùwà kan

    Térú wa á domo


    Èetirí!! Èetijé !!?

     Eeyé fara niwá món

    Oba òkè ti fúnwa lóun àlúmooni tó yeewa,ósewá jépé,ara wa laafi  n nilara


    Epo won gógó,aféfé gaasi òosé kolù loja

    Naira owó ilè yí wá di pónkan lágbayé ejé áronú ká pínwà dà


    Ominú komí pé ,ùnjé oun rere kan a ti lè ti Jerusalem naija jáde wá món?

    Èyin àgbà  e dákun ebá mi fèsì sórò tógbàpérò


    Àfí kélédùà óbáwa dási kótó burú jai


    Mojísé Orí ránmi, àbò lódààà




    Gbogbo ẹtọ wa ni ipamọ. O ko ni ẹtọ lati tun tabi ṣe atẹjade eyikeyi akoonu lati oju opo wẹẹbu yii laisi igbanilaaye kikọ lati ọdọ NEB. 



    Kan si Olootu;@NAMACOSONLINE

    No comments